Àkọsílẹ̀ Lúùkù 16:1-31

  • Àpèjúwe ìríjú aláìṣòdodo (1-13)

    • “Ẹni tó bá jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun tó kéré jù jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun tó pọ̀” (10)

  • Òfin àti Ìjọba Ọlọ́run (14-18)

  • Àpèjúwe ọkùnrin ọlọ́rọ̀ àti Lásárù (19-31)

16  Ó tún wá sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn pé: “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan ní ìríjú* kan, tí wọ́n fẹ̀sùn kàn pé ó ń fi àwọn ẹrù ọ̀gá rẹ̀ ṣòfò.  Torí náà, ó pè é, ó sì sọ fún un pé, ‘Kí ni mo gbọ́ pé o ṣe yìí? Gbé àkọsílẹ̀ iṣẹ́ ìríjú rẹ wá, torí o ò lè bójú tó ilé yìí mọ́.’  Ìríjú náà wá sọ fún ara rẹ̀ pé, ‘Kí ni kí n ṣe, ní báyìí tí ọ̀gá mi fẹ́ gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi? Mi ò lágbára tó láti gbẹ́lẹ̀, ojú sì ń tì mí láti ṣagbe.  Áà! Mo mọ ohun tí màá ṣe, kó lè jẹ́ pé tí wọ́n bá gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi, àwọn èèyàn máa gbà mí sínú ilé wọn.’  Ó wá pe ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn tó jẹ ọ̀gá rẹ̀ ní gbèsè, ó sì sọ fún ẹni àkọ́kọ́ pé, ‘Èló lo jẹ ọ̀gá mi?’  Ó fèsì pé, ‘Ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n* òróró ólífì.’ Ó sọ fún un pé, ‘Gba ìwé àdéhùn tí o kọ pa dà, jókòó, kí o sì kọ àádọ́ta (50) kíákíá.’  Lẹ́yìn náà, ó sọ fún ẹlòmíì pé, ‘Ìwọ, èló ni gbèsè tí o jẹ?’ Ó ní, ‘Ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n ńlá* àlìkámà.’* Ó sọ fún un pé, ‘Gba ìwé àdéhùn tí o kọ pa dà, kí o sì kọ ọgọ́rin (80).’  Bó tiẹ̀ jẹ́ pé aláìṣòdodo ni ìríjú náà, ọ̀gá rẹ̀ yìn ín, torí pé ó lo ọgbọ́n tó gbéṣẹ́;* torí àwọn ọmọ ètò àwọn nǹkan yìí* gbọ́n féfé sí ìran tiwọn ju àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀ + lọ.  “Bákan náà, mò ń sọ fún yín pé: Ẹ fi ọrọ̀ àìṣòdodo wá ọ̀rẹ́ fún ara yín,+ kó lè jẹ́ pé, tó bá kùnà, wọ́n máa lè gbà yín sínú àwọn ibùgbé ayérayé.+ 10  Ẹni tó bá jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun tó kéré jù jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun tó pọ̀ pẹ̀lú, ẹni tó bá sì jẹ́ aláìṣòdodo nínú ohun tó kéré jù jẹ́ aláìṣòdodo nínú ohun tó pọ̀ pẹ̀lú. 11  Torí náà, tí ẹ kò bá tíì fi hàn pé olóòótọ́ ni yín tó bá kan ọrọ̀ àìṣòdodo, ta ló máa fi ohun tó jẹ́ òtítọ́ sí ìkáwọ́ yín? 12  Tí ẹ kò bá sì tíì fi hàn pé olóòótọ́ ni yín tó bá kan ohun tó jẹ́ ti ẹlòmíì, ta ló máa fún yín ní nǹkan pé kó jẹ́ tiyín?+ 13  Kò sí ìránṣẹ́ tó lè jẹ́ ẹrú ọ̀gá méjì, àfi kó kórìíra ọ̀kan, kó sì nífẹ̀ẹ́ ìkejì tàbí kó fara mọ́ ọ̀kan, kó má sì ka ìkejì sí. Ẹ ò lè jẹ́ ẹrú Ọlọ́run àti Ọrọ̀.”+ 14  Àwọn Farisí, tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ owó, ń fetí sí gbogbo nǹkan yìí, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í yínmú sí i.+ 15  Torí náà, ó sọ fún wọn pé: “Ẹ̀yin lẹ̀ ń kéde pé olódodo ni yín níwájú àwọn èèyàn,+ àmọ́ Ọlọ́run mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.+ Torí ohun tí àwọn èèyàn kà sí ohun tí a gbé ga jẹ́ ohun ìríra lójú Ọlọ́run.+ 16  “Òfin àti àwọn Wòlíì wà títí dìgbà Jòhánù. Látìgbà yẹn lọ, à ń kéde Ìjọba Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ìhìn rere, onírúurú èèyàn sì ń fi agbára lépa rẹ̀.+ 17  Ní tòótọ́, ó rọrùn kí ọ̀run àti ayé kọjá lọ ju kí ìlà kan lára lẹ́tà inú Òfin lọ láìṣẹ.+ 18  “Gbogbo ẹni tó bá kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, tó sì fẹ́ ẹlòmíì ti ṣe àgbèrè, ẹnikẹ́ni tó bá sì fẹ́ obìnrin tí ọkọ rẹ̀ kọ̀ sílẹ̀ ti ṣe àgbèrè.+ 19  “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà tó máa ń wọ aṣọ aláwọ̀ pọ́pù àti aṣọ ọ̀gbọ̀,* ojoojúmọ́ ló ń gbádùn ara rẹ̀ dọ́ba. 20  Àmọ́ wọ́n máa ń gbé alágbe kan tó ń jẹ́ Lásárù sí ẹnubodè rẹ̀, egbò wà ní gbogbo ara rẹ̀, 21  ó sì máa ń wù ú pé kó jẹ lára àwọn nǹkan tó ń já bọ́ látorí tábìlì ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà. Àní àwọn ajá pàápàá máa ń wá pọ́n àwọn egbò rẹ̀ lá. 22  Nígbà tó yá, alágbe náà kú, àwọn áńgẹ́lì sì gbé e lọ sí ẹ̀gbẹ́* Ábúráhámù. “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yẹn náà kú, wọ́n sì sin ín. 23  Ó gbé ojú rẹ̀ sókè nínú Isà Òkú,* ó ń joró, ó wá rí Ábúráhámù ní ọ̀ọ́kán, ó sì rí Lásárù ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.* 24  Torí náà, ó pè é, ó sì sọ pé, ‘Ábúráhámù baba, ṣàánú mi, kí o sì rán Lásárù pé kó ki orí ìka rẹ̀ bọ omi, kó sì mú kí ahọ́n mi tutù, torí mò ń jẹ̀rora nínú iná tó ń jó yìí.’ 25  Àmọ́ Ábúráhámù sọ pé, ‘Ọmọ, rántí pé ìwọ gbádùn ohun rere dáadáa nígbà ayé rẹ, àmọ́ ohun burúkú ni Lásárù gbà ní tiẹ̀. Ní báyìí, ó ń gba ìtura níbí, àmọ́ ìwọ ń jẹ̀rora. 26  Yàtọ̀ sí gbogbo nǹkan yìí, a ti mú kí ọ̀gbun ńlá kan wà láàárín àwa àti ẹ̀yin, kí àwọn tó fẹ́ lọ sọ́dọ̀ yín láti ibí má bàa kọjá, kí àwọn èèyàn má sì kọjá láti ibẹ̀ yẹn sọ́dọ̀ wa.’ 27  Ó wá sọ pé, ‘Tó bá rí bẹ́ẹ̀, mo bẹ̀ ọ́, baba, pé kí o rán an sí ilé bàbá mi, 28  torí mo ní arákùnrin márùn-ún, kó lè jẹ́rìí kúnnákúnná fún wọn, kí àwọn náà má bàa wá sínú ibi oró yìí.’ 29  Àmọ́ Ábúráhámù sọ pé, ‘Wọ́n ní Mósè àti àwọn Wòlíì; kí wọ́n fetí sí àwọn yìí.’+ 30  Ó wá sọ pé, ‘Rárá o, Ábúráhámù baba, àmọ́ tí ẹnì kan tó ti kú bá lọ sọ́dọ̀ wọn ní tòótọ́, wọ́n máa ronú pìwà dà.’ 31  Àmọ́ ó sọ fún un pé, ‘Tí wọn ò bá fetí sí Mósè+ àti àwọn Wòlíì, wọn ò lè yí èrò wọn pa dà tí ẹnì kan tó ti kú bá tiẹ̀ dìde.’”

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “alábòójútó ilé.”
Tàbí “báàtì.” Báàtì kan jẹ́ Lítà 22 (gálọ́ọ̀nù 5.81). Wo Àfikún B14.
Tàbí “Ọgọ́rùn-ún òṣùwọ̀n kọ́ọ̀.” Kọ́ọ̀ kan jẹ́ Lítà 220. Wo Àfikún B14.
Tàbí “wíìtì.”
Tàbí “fi ọgbọ́n hùwà; fi òye hùwà.”
Tàbí “àsìkò yìí.” Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “aṣọ àtàtà.”
Ní Grk., “oókan àyà.”
Tàbí “Hédíìsì,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Ní Grk., “ní oókan àyà rẹ̀.”