MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Ohun Tí Mo Lè Ṣe Táá Jẹ́ Ká Túbọ̀ Lórúkọ Rere
Àwọn èèyàn máa ń kíyè sí ìwà àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà. (1Kọ 4:9) A lè bi ara wa pé, ‘Ṣé ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti ìwà mi ń bọlá fún Jèhófà?’ (1Pe 2:12) Ọjọ́ pẹ́ táwọn èèyàn ti mọ̀ pé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní orúkọ rere, ó sì dájú pé a ò ní fẹ́ ṣe ohunkóhun tó máa ba orúkọ rere wa jẹ́.—Onw 10:1.
Nínú àwọn ipò tá a tò sísàlẹ̀ yìí, kọ ohun tó yẹ kí Kristẹni kan ṣe àti ìlànà Bíbélì tó lè ràn án lọ́wọ́:
-
Ẹnì kan tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà fìbínú sọ̀rọ̀ sí ẹ
-
Tí mọ́tò rẹ bá dọ̀tí, tí ilé rẹ ò ṣeé rí tàbí tí aṣọ ẹ rí wúruwùru
-
Ìjọba ṣòfin kan tó ṣòro fún ẹ láti pa mọ́
Báwo làwọn tó ń ṣèwádìí ní Ẹ̀ka Ìwé Kíkọ ṣe ń mú ká túbọ̀ ní orúkọ rere?
Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ A NÍFẸ̀Ẹ́ ÒTÍTỌ́, A SÌ NÍ Ọ̀WỌ̀ TÓ JINLẸ̀ FÚN ÒTÍTỌ́, KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
Kí ló wú ẹ lórí nínú gbogbo ohun tí ètò Ọlọ́run ń ṣe láti rí i dájú pé ohun tó péye tó sì jẹ́ òótọ́ là ń tẹ̀ jáde?